Wọ́n Sun Ìgbẹ́jọ́ Ẹjọ́ Nnamdi Kanu Síwájú, NMA Ṣì Ń Ṣe Àyẹ̀wò
Adájọ́ James Omotosho ti Ilé Ẹjọ́ Gbẹ́rẹ̀ Ìjọba Àpapọ̀ ní Abuja, ti sun ìgbẹ́jọ́ aṣáájú Indigenous People of Biafra (IPOB), Nnamdi Kanu, síwájú di Oṣù Kẹ̀wá Ọjọ́ Kẹrindínlógún (October 16th).
Ìdí fún sísun síwájú yìí ni pé Nigerian Medical Association (NMA) kò tíì lè parí àyẹ̀wò tí wọ́n ń ṣe lórí bí Ọ̀gbẹ́ni Kanu ṣe wà lára àti gbígbé ìròyìn rẹ̀ kalẹ̀ níwájú ilé ẹjọ́.
Adájọ́ Omotosho ti pa àṣẹ fún Ààrẹ NMA nígbà ìgbẹ́jọ́ tó kọjá pé kí ó dá ìgbìmọ̀ àwọn onímọ̀ ìṣègùn kan sílẹ̀ láti ṣe ìwádìí lórí ẹ̀sùn pé àìsàn olùjìyà náà ń pọ̀ sí i.
Ète àyẹ̀wò ìṣègùn yìí ni láti mọ̀ bóyá ibùdó ìṣègùn tó wà ní orílé-iṣẹ́ Department of the State Service (DSS) lè tọ́jú Ọ̀gbẹ́ni Kanu tàbí bóyá wọ́n gbọ́dọ̀ gbé e lọ sí National Hospital gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gbẹ́ni Kanu ti béèrè.
Ìròyìn náà yóò tún pinnu bóyá Ọ̀gbẹ́ni Kanu lágbára láti tẹ̀síwájú nínú ìgbẹ́jọ́ rẹ̀.
Níbi ìgbẹ́jọ́ ọjọ́ náà, Suraj S’aad SAN, amòfin fún ìjọba, sọ fún ilé ẹjọ́ pé Ìgbìmọ̀ Ìṣègùn náà ti sọ fún wọn pé ìròyìn náà kò tíì ṣe tán láti gbé kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ilé ẹjọ́.
Amòfin àgbà náà wá fi lẹ́tà tọrọ pé kí wọ́n sun ìgbẹ́jọ́ náà síwájú fún ọ̀sẹ̀ kan láti jẹ́ kí Ìgbìmọ̀ Ìṣègùn NMA parí ìwádìí rẹ̀.
Lẹ́yìn tí Onyechi Ikpeazu, amòfin fún olùjìyà náà, kò fi ìgbólóhùn kọ ìbèèrè ìsun síwájú náà, Adájọ́ Omotosho pinnu Oṣù Kẹ̀wá Ọjọ́ Kẹrindínlógún (October 16th) fún ìgbìmọ̀ náà láti gbé ìròyìn rẹ̀ kalẹ̀ àti láti pinnu ìgbésẹ̀ tí yóò tẹ̀ lé e.
editor's pick
latest video
news via inbox
Nulla turp dis cursus. Integer liberos euismod pretium faucibua

