Sẹ́nátọ̀ Natasha Darapọ̀ Mọ́ Ìpolongo #JusticeForOchanya

Sẹ́nátọ̀ Natasha Akpoti-Uduaghan (PDP, Kogi Central) ti darapọ̀ mọ́ ìpè tuntun fún ìdájọ́ òdodo lórí ọ̀rọ̀ ọmọdébìnrin ọmọ ọdún mẹ́tàlá (13), Ochanya Ogbanje, ẹni tí ó pàdánù ẹ̀mí rẹ̀ lọ́nà tí ó banújẹ́ ní ọdún 2018 lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún tí wọ́n fi ń fura sí pé wọ́n ń ṣe ìfipábáni-lòpọ̀ fún.

Ìfipábáni-lòpò náà, tí wọ́n ròyìn pé ẹ̀gbọ́n bàbá Ochanya, Andrew Ogbuja, àti ọmọ rẹ̀, Victor, ṣe ní Ìpínlẹ̀ Benue, ru ìbínú orílẹ̀-èdè káàkiri, ó sì mú kí àwọn ẹgbẹ́ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn pè fún òfin tó le sí i láti dáàbò bo àwọn ọmọdé kúrò nínú gbogbo irú ìfipábani-lòpọ̀.

Nínú ìwé tí ó tẹ̀ jáde lórí ojú-ìwé Facebook rẹ̀ ní Ọjọ́bọ̀ (Thursday), Sẹ́nátọ̀ Akpoti-Uduaghan fi ìbànújẹ́ rẹ̀ hàn pé àwọn tí wọ́n fura sí pé wọ́n ṣe ẹ̀ṣẹ̀ náà ṣì wà ní òmìnira.

Ó sọ pé, “Ní ọdún méje (7) sẹ́yìn, ìtàn ọmọdé Ochanya fọ́ ọkàn mi. Mo rò pé àwọn tí ó ṣe ẹ̀ṣẹ̀ náà wà lẹ́wọ̀n. Àbà, wọ́n tú wọn sílẹ̀, wọ́n sì dá wọn láre.”

Ó fìdí ìtìlẹ́yìn rẹ̀ múlẹ̀ fún ìdájọ́ òdodo, ó sọ pé, “Nítorí àwọn ọmọ wa, mo dúró fún ìdájọ́ òdodo fún Ochanya,” nígbà tí ó dúpẹ́ lọ́wọ́ ajíjàgbara lórí ẹ̀rọ ayélujára, #miss_natural1, fún mímú ọ̀rọ̀ náà wá sí ìtẹ́tísí rẹ̀.

Ìpolongo #JusticeForOchanya ti tún gba agbára tuntun lórí ẹ̀rọ ayélujára, níbi tí àwọn ọmọ Nàìjíríà ti ń pè fún wíwádìí àti ìdájọ́ òdodo fún ọmọdébìnrin tí ó ti kú náà.

Sẹ́nátọ̀ Natasha rọ ìdílé Ochanya láti fi ẹ̀bẹ̀ àkọsílẹ̀ sílẹ̀ ní ọ́fíìsì rẹ̀ ní Room 2:05, Senate Wing, National Assembly Complex, Abuja, ó sì ṣe ìlérí láti gbé ọ̀rọ̀ náà lọ síwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ nínú Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àgbà.

editor's pick

latest video

Mail Icon

news via inbox

Nulla turp dis cursus. Integer liberos  euismod pretium faucibua

Leave A Comment